Job 24:22-24
Job 24:22-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní (YCB)
Ọlọ́run fi ipá agbára rẹ̀ fa alágbára, bí wọ́n tilẹ̀ fìdímúlẹ̀, kò sí ìrètí ìyè fún wọn. Ọlọ́run sì fi àìléwu fún un, àti nínú èyí ni a ó sì tì i lẹ́yìn, ojú rẹ̀ sì wà ní ipa ọ̀nà wọn. A gbé wọn lékè nígbà díẹ̀, wọ́n kọjá lọ; a sì rẹ̀ wọ́n sílẹ̀; A sì mú wọn kúrò ní ọ̀nà bí àwọn ẹlòmíràn, a sì ké wọn kúrò bí orí síírí ọkà bàbà.
Job 24:22-24 Bibeli Mimọ (YBCV)
O fi ipá rẹ̀ fà alagbara lọ pẹlu; o dide, kò si ẹniti ẹmi rẹ̀ da loju. On si fi ìwa ailewu fun u, ati ninu eyi ni a o si tì i lẹhin, oju rẹ̀ si wà ni ipa-ọna wọn. A gbe wọn lekè nigba diẹ, nwọn kọja lọ, a si rẹ̀ wọn silẹ, a si mu wọn kuro li ọ̀na, bi awọn ẹlomiran, a si ke wọn kuro bi ori ṣiri itú ọkà bàbà.
Job 24:22-24 Yoruba Bible (YCE)
Sibẹsibẹ Ọlọrun fi ẹ̀mí gígùn fún alágbára nípa agbára rẹ̀; wọn á gbéra nígbà tí ayé bá sú wọn. Ọlọrun ń dáàbò bò wọ́n, ó ń ràn wọ́n lọ́wọ́, ó sì ń pa wọ́n mọ́ ni ọ̀nà wọn. A gbé wọn ga fún ìgbà díẹ̀, lẹ́yìn náà, a rẹ̀ wọ́n sílẹ̀, wọn á rọ, wọn á sì rẹ̀ dànù bí ewé, a ké wọn kúrò bí orí ọkà bàbà.