Àmì Ìdánimọ̀ Ohun-èlò Bíbélì
Ṣe Àwárí

Ṣe àfiwé gbogbo èyà

Esek 8:3YBCV(Bibeli Mimọ)

O si nà àworan ọwọ́ jade, o si mu mi ni ìdi-irun ori mi; ẹmi si gbe mi soke lagbedemeji aiye on ọrun, o si mu mi wá ni iran Ọlọrun si Jerusalemu, si ilẹkun ẹnu-ọ̀na ti inu to kọju si ariwa; nibiti ijoko ere owu wà ti nmu ni jowu.

Esek 8:3BMYO(Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní)

Ó na ohun tó dàbí ọwọ́ jáde, ó fi gba mi ní irun orí mú, Ẹ̀mí sì gbé mi sókè sí agbede-méjì ayé àti ọ̀run, ó sì mú mi lọ rí ìran Ọlọ́run, mo sì lọ sí Jerusalẹmu, ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òde àríwá níbi tí ère owú tí ó ń mú ni bínú wá níwájú mi.

Esek 8:3YCE(Yoruba Bible)

Ó na nǹkankan tí ó dàbí ọwọ́, ó fi gbá ìdí irun orí mi mú, ẹ̀mí sì gbé mi sókè sí agbede meji ọ̀run ati ayé, ó gbé mi lọ sí Jerusalẹmu, ninu ìran Ọlọrun, ó gbé mi sí ẹnu ọ̀nà àgbàlá gbọ̀ngàn ti inú tí ó kọjú sí ìhà àríwá, níbi tí wọ́n gbé ère tí ń múni jowú sí.