1
Saamu 95:6-7
Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde-Òní
BMYO
Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a foríbalẹ̀ kí a sìn ín, ẹ jẹ́ kí a kúnlẹ̀ níwájú OLúWA ẹni tí ó dá wa, nítorí òun ni Ọlọ́run wa, àwa sì ni ènìyàn pápá rẹ̀, àti ọ̀wọ́ ẹran ni abẹ́ ìpamọ́ rẹ̀. Lónìí tí ìwọ bá gbọ́ ohùn rẹ̀
Ṣe Àfiwé
Ṣàwárí Saamu 95:6-7
2
Saamu 95:1-2
Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a kọ orin ayọ̀ sí OLúWA, ẹ jẹ́ kí a kígbe sókè sí àpáta ìgbàlà wa. Ẹ jẹ́ kí a wá sí iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ọpẹ́ kí a sì pòkìkí rẹ̀ pẹ̀lú ohun èlò orin àti ìyìn.
Ṣàwárí Saamu 95:1-2
3
Saamu 95:3
Nítorí OLúWA Ọlọ́run títóbi ni, ọba tí ó tóbi ju gbogbo òrìṣà lọ.
Ṣàwárí Saamu 95:3
4
Saamu 95:4
Ní ọwọ́ rẹ̀ ni ọ̀gbun ilẹ̀ wà, ṣóńṣó orí òkè tirẹ̀ ní ṣe.
Ṣàwárí Saamu 95:4