Àmì Ìdánimọ̀ Ohun-èlò Bíbélì
Ṣe Àwárí

Saamu 114

114
Saamu 114
1Nígbà tí Israẹli jáde ní Ejibiti,
ilé Jakọbu láti inú ènìyàn àjèjì èdè
2Juda wà ní ibi mímọ́,
Israẹli wà ní ìjọba.
3 Òkun sì rí i, ó sì wárìrì:
Jordani sì padà sẹ́yìn.
4Àwọn òkè ńlá ń fò bí àgbò àti
òkè kéékèèké bí ọ̀dọ́-àgùntàn.
5Kí ni ó ṣe ọ́, ìwọ Òkun, tí ìwọ fi wárìrì?
Ìwọ Jordani, tí ìwọ fi padà sẹ́yìn?
6Ẹ̀yin òkè ńlá kí ló dé ti ẹ fi ń fò bí àgbò,
àti ẹ̀yin òkè kéékèèké bí ọ̀dọ́-àgùntàn?
7Wárìrì, ìwọ ilẹ̀, níwájú Olúwa;
ní iwájú Ọlọ́run Jakọbu
8tí ó sọ àpáta di adágún omi,
àti òkúta-ìbọn di orísun omi.

Àwon tá yàn lọ́wọ́lọ́wọ́ báyìí:

Saamu 114: BMYO

Ìsàmì-sí

Daako

Ṣe Àfiwé

Pín

None

Ṣé o fẹ́ fi àwọn ohun pàtàkì pamọ́ sórí gbogbo àwọn ẹ̀rọ rẹ? Wọlé pẹ̀lú àkántì tuntun tàbí wọlé pẹ̀lú àkántì tí tẹ́lẹ̀