Àmì Ìdánimọ̀ Ohun-èlò Bíbélì
Ṣe Àwárí

Saamu 93

93
Saamu 93
1 Olúwa ń jẹ ọba, ọláńlá ni ó wọ̀ ní aṣọ;
ọláńlá ni Olúwa wọ̀ ní aṣọ
àti ìhámọ́ra rẹ̀ pẹ̀lú agbára.
Ó fi ìdí ayé múlẹ̀;
kò sì le è yí.
2Ìjọba rẹ̀ wà láti ọjọ́ pípẹ́;
ìwọ wà títí ayérayé.
3A ti gbé òkun sókè, Olúwa,
òkun ti gbé ohùn wọn sókè;
òkun ti gbé rírú omi wọn sókè.
4Ó ni ògo ju àrá omi ńlá lọ,
ó ni ògo ju òkun rírú lọ
Olúwa ga ní ògo.
5Ẹ̀rí rẹ̀ dúró ṣinṣin;
ìwà mímọ́ ni ó fi ṣe ilé rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́
fún ọjọ́ àìlópin, Olúwa.

Àwon tá yàn lọ́wọ́lọ́wọ́ báyìí:

Saamu 93: BMYO

Ìsàmì-sí

Daako

Ṣe Àfiwé

Pín

None

Ṣé o fẹ́ fi àwọn ohun pàtàkì pamọ́ sórí gbogbo àwọn ẹ̀rọ rẹ? Wọlé pẹ̀lú àkántì tuntun tàbí wọlé pẹ̀lú àkántì tí tẹ́lẹ̀